Eto eko ni orile-ede Naijiria

Students at a public school in Kwara State

Àdàkọ:Infobox Education Ètò ẹ̀kọ́ ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ni ó wà ní abẹ̀ ̀akóso aj̀ọ tí ó ń rísí ètò-èkó ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ti a mọ sí Federal Ministry of Education.[1] Àwọn ìjọba ìbílẹ̀ kọ̀ọ̀kan ni wọ́n ń ṣe ìmúṣẹ àgbékalẹ̀ ìlànà ètò-ẹ̀kó tí ìjọba ìpínlẹ̀ wọn bá gbé kalẹ̀ fún lílò ní àwọn ilé-ẹ̀kọ́ ìjọba ìpínlẹ̀ àti ti gbogbo-gbòò .[2] Ìlànà ìkọ́ni ní orílè-èdè Nàìjíríà pín sí ọ̀nà mẹ́ta. Àkọ́kọ́ ni ilé-ẹ̀kọ́ jẹ́lé-ó-sinmin, èkejì ni ilé-ẹ̀kọ́ alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀, ẹ̀kẹta ni ilé-ẹ̀kọ́ girama, nígbà tí ẹ̀kẹrin jẹ́ ilé-ẹ̀kọ́ àgbà.[3] Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wípé ìjọba ni ó ń ṣ'àkóso ètò ẹ̀kọ́, àwọn ilé-ẹ̀kọ́ ìjọba gbogbo ni wọn kò fi bẹ́ẹ̀ dúró ṣinṣin láti ìgbà tí ìjọba orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ti gba òmìnira kúrò lọ́wọ̀ àwọn gẹ̀ẹ́sì bìrìtìkó, síbẹ̀, ètò ẹ̀kọ́ kárí-ayé tí ò gúnmọ́ kò tíì fẹsẹ̀ múlẹ̀ ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà láti ìgbà náà wá.[4] Oríṣiríṣi ìyàtọ̀ ni ó wà nìnú ìlànà àtẹ ètò-ẹ̀kọ́, tí owó níná sì ètò ẹ̀kọ́ náà sì tún ń ṣ'àkóóbá fun pẹ̀lú.[5][6] Lọwọlọwọ bayi, orilẹ-eded Naigiria ni o ni awọn ọmọ ti wọn ko si ni ile-ẹkọ julọ ni orile agbaye.[6] Oríṣi ilé-ẹ̀kọ́ méjì ni ó wà ní orìlẹ̀-èdè Nàìjíríà, àkọ́kọ́ ni ilé-ẹ̀kọ́ ìjọba, èkejì ni ilé ẹ̀kọ́ aládàáni [7] Ètò ẹ̀kọ́ ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ni wọ́n ma ń fi èdè gẹ̀ẹ́sì ṣe àgbékalẹ̀ rẹ̀ fún àwọn akẹ́kọ̀ọ́. Àmọ́, ní ọgbọ̀nọjọ́ oṣù kọkànlá ọdún 2022 ni mínísítà fún ètò ẹ̀kọ́, ọ̀gbẹ́ni Adamu Adamu kéde wípe ìjọba ń gbèrò láti dẹ́kun lílo èdè gẹ̀ẹ́sì fún ìgbèkọ́ ní àwọn ilé-èkọ́ aĺakọ̀ọ́bẹ̀rẹ ̀gbogbo kí wọ́n sì fi èdè abínibí tí wón bá ń ṣàmúlò rẹ̀ ní agbègbè tí ilé-ẹ̀kọ́ náà bá wà ní orílẹ̀-èdè Nàìjírìà.[8]

  1. "Home". FEDERAL MINISTRY OF EDUCATION (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2021-05-17. 
  2. "Education System in Nigeria and How Far We Have Gone: A brief History : Study Driller". www.studydriller.com. Retrieved 2020-05-26. 
  3. Glavin, Chris (2017-02-07). "Education in Nigeria". k12academics.com (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2020-05-27. 
  4. Ajibade, B.O. (2019). "Knowledge and Certificate based System: A Critical Analysis of Nigeria's Educational System". Global Journal of Human-Social Science, Linguistics and Education 19 (8). Archived from the original on 21 July 2020. https://web.archive.org/web/20200721025750/https://socialscienceresearch.org/index.php/GJHSS/article/download/2995/2884. Retrieved 2 April 2024. 
  5. Aminu, Jibril (1990). "Education in Nigeria: Overcoming Adversity". Journal of Education Finance 15 (4): 581–586. JSTOR 40703846. 
  6. 6.0 6.1 Abdullahi, Danjuma; Abdullah, John (June 2014). "The Political Will and Quality Basic Education in Nigeria". Journal of Power, Politics, and Governance 2 (2): 75–100. Archived from the original on 2020-11-13. https://web.archive.org/web/20201113071011/http://jppgnet.com/journals/jppg/Vol_2_No_2_June_2014/5.pdf. Retrieved 2024-04-02. 
  7. "Nigeria's public school system, a blow". The Guardian Nigeria News - Nigeria and World News (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 2019-11-27. Retrieved 2021-09-23. 
  8. "Nigeria to abolish English language for teaching in primary schools". Africanews (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 2022-12-01. Retrieved 2022-12-15. 

From Wikipedia, the free encyclopedia · View on Wikipedia

Developed by Nelliwinne