Rachel Sophia Baard jẹ́ ẹlẹ́kọ̀ó ẹ̀sìn ti orílẹ̀-èdè South African. Láti ọdún 2019, ó jẹ́ ọ̀jọ̀gbọ́n ti Theology and Ethics ní Union Theological Seminary ní Richmond, Virginia, United States.[1][2] Ìwé rẹ̀ àkọ́kọ́, ìyẹn Sexism and Sin-Talk: Feminist Conversations on the Human Condition (2019) gba àmì-ẹ̀yẹ ti 2020 Andrew Murray / Desmond Tutu Book Prize.[2] Àwọn iṣé-ìwádìí rẹ̀ dá lórí ẹ̀kọ́ ẹ̀sìn ní ṣísẹ̀-n-tẹ̀lé, ẹ̀kọ́ ìwà ajẹmẹ́sìn, ìṣègbèfábo àti ẹ̀kọ́ ẹ̀sìn ajẹmọ́-ìṣèlú.[3]
Ilé-ẹ̀kọ́ Stellenbosch University ni ó ti jáde, pẹ̀lú oyè ẹ̀kọ́ nínú ìmọ̀ òfin àti ẹ̀kọ́ ìwà ajẹmẹ́sìn. Ó gba oyè Ph.D. ti ẹ̀kọ́ ẹ̀sìn ní ṣísẹ̀-n-tẹ̀lé láti Princeton Theological Seminary. Lẹ́yìn náà ni ó lọ sí Richmond, ní kété tí ó ṣiṣẹ́ olùkọ́ ní Villanova University.[2][3]